Saamu 126
Orin fún ìgòkè.
Nígbà tí Olúwa mú ìkólọ Sioni padà,
àwa dàbí ẹni tí ó ń lá àlá.
Nígbà náà ni ẹnu wa kún fún ẹ̀rín,
àti ahọ́n wa kọ orin;
nígbà náà ni wọ́n wí nínú àwọn kèfèrí pé,
Olúwa ṣe ohun ńlá fún wọn.
Olúwa ṣe ohun ńlá fún wa;
nítorí náà àwa ń yọ̀.
 
Olúwa mú ìkólọ wa padà,
bí ìṣàn omi ní gúúsù.
Àwọn tí ń fi omijé fún irúgbìn
yóò fi ayọ̀ ka.
Ẹni tí ń fi ẹkún rìn lọ,
tí ó sì gbé irúgbìn lọ́wọ́,
lóòtítọ́, yóò fi ayọ̀ padà wá,
yóò sì ru ìtí rẹ̀.